Hedayat “A fruitful harvest”
from the gardens of “ Verses and Hadiths ”
Inspiring Dawah cards that highlight the profound meanings of Quranic verses and Prophetic Hadiths. Presented in an accessible and engaging style to help Muslims gain a deeper understanding of their faith with ease.
About Hedayat
Hedayat is a platform that combines simplicity of design and ease of use
displaying the benefits derived from Verses and Hadiths in
attractive cards with unique designs.
Unique Designs
Cards with unique and attractive designs that express the content of the text
Reliable Materials
Scientifically reliable benefits reviewed by a group of scholars
Easy Browsing
You can browse the cards easily and display them effortlessly
Different Languages
Cards are available in more than 40 languages for the benefit of all
Hadith Cards
Lati ọdọ Abu Musa Al-Ash’ariy- ki Ọlọhun yọnu si i- lati ọdọ Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o sọ pe: “Ẹ maa ka Kuraani yii ni ìgbà gbogbo, mo fi Ẹni tí ẹmi Muhammad n bẹ lọ́wọ́ Rẹ bura, o yara sá lọ ju ràkúnmí ninu okùn ti wọn fi dè é lọ”.
Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí niAnọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- pàṣẹ ki a maa ka Kuraani nígbà gbogbo, ki a si maa tẹra mọ́ kika a ki èèyàn ma baa gbagbe rẹ lẹyin híhá a, o wa tẹnu mọ́ ọn pẹ̀lú ìbúra pe Kuraani yára kuro ninu àyà ju rakunmi ti a so lọ, oun naa ni eyi ti a fi okùn dè ni aarin ẹsẹ, ti eeyan ba n ka a nígbà gbogbo, o maa di i mu, ti o ba si tu u sílẹ̀, o maa lọ.
Lati ọdọ Abdullāh ọmọ Mas‘ūd – ki Ọlọhun yọnu si i – o sọ pe: Ojiṣẹ Ọlọhun – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – sọ pe: «Ẹni ti o ba ka harafi kan ninu tira Ọlọhun, o maa fi gba ẹsan daada kan, ati pe ẹsan kan yio maa ni ilọpo mẹwaa iru rẹ, mi o sọ wipe “alif lām mīm” harafi kan ni o, amọ alifu harafi kan ni, lāmu naa harafi kan ni, mīmu naa harafi kan ni».
Tirmiziy ni o gba a waAnabi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – sọ wípé dajudaju gbogbo Musulumi kọọkan ti o ba n ka harafi kan ninu tira Ọlọhun ni ẹsan kọọkan a máa bẹ fun un, ti wọn yio si ṣe adipele ẹsan naa fun un ni ilọpo mẹwaa iru rẹ. Lẹyin naa ni o wa ṣalaye pẹlu gbolohun rẹ ti o sọ pe: (Mi o sọ wipe “alif lām mīm” harafi kan ni o, amọ alif harafi kan ni, lām naa harafi kan ni, mīm naa harafi kan ni): Nítorí naa yio jẹ harafi mẹta ti o ko ẹsan ọgbọn sinu.
Lati ọdọ Abu Musa Al-ash’ari - ki Ọlọhun yọnu si i - ó sọ pé: Ojiṣẹ Ọlọhun - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - sọ pé: “Àpèjúwe Mumini ti n ka Kuraani da gẹgẹ bii èso utrujjah, ti oorun rẹ daa, ti itọwo rẹ naa si daa, àpèjúwe mumini ti kii ka Kuraani da gẹgẹ bii èso dabinu, ti ko ni oorun, ti itọwo rẹ si dùn, àpèjúwe munaafiki ti n ka Kuraani da gẹgẹ bii èso rayhaanah, ti oorun rẹ dùn, ti itọwo rẹ si korò, àpèjúwe munaafiki ti kii ka Kuraani da gẹgẹ bii èso hansọla, ti ko ni oorun, ti itọwo rẹ tún korò".
Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí niOjiṣẹ Ọlọhun, ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a, ṣe alaye àwọn ìpín awọn eniyan nipa kika Al-Qur’an ati jijẹ anfaani rẹ: Ìpín akọkọ: Mumini ti n ka Kuraani ti o si n ṣe àǹfààní pẹ̀lú rẹ, o da gẹgẹ bii èso utrujjah, ti itọwo ati oorun rẹ daa, ti awọ rẹ si daa, ti anfaani rẹ si pọ̀, o n lo nnkan ti o n ka, o si n ṣe awọn ẹru Ọlọhun ni anfaani. Ìkejì: Mumini ti kii ka Kuraani, o da gẹgẹ bii èso dabinu, itọwo rẹ dun, ko si ni oorun, ọkàn rẹ ko ìgbàgbọ́ sínú, gẹgẹ bi eso dabinu ṣe ko adun sinu nibi itọwo rẹ ati inú rẹ, ati aihan oorun rẹ ti àwọn èèyàn a gbọ́; torí aihan kika rẹ ti awọn eeyan le fi àyà balẹ si gbigbọ rẹ. Ikẹta: Munaafiki ti n ka Kuraani, o da bii eso rayhaanah, ti oorun rẹ daa ti itọwo rẹ korò, torí igbagbọ ko tun ọkàn rẹ ṣe, ko si lo Kuraani, o wa n ṣe bii mumini loju àwọn èèyàn, oorun rẹ ti o daa jọ kika a, itọwo rẹ ti o korò si jọ iṣe Kèfèrí rẹ. Ikẹrin: Munaafiki ti kii ka Kuraani, o da bii eso hansọla, ko ni oorun, itọwo rẹ si korò, àìní oorun rẹ jọ aika rẹ, ìkorò itọwo rẹ jọ ìkorò ìṣe Kèfèrí rẹ, ko si igbagbọ ninu rẹ, òde rẹ naa o ṣe anfaani, bi ko ṣe pe o tun n ko inira bani ni.
Lati ọdọ 'Adiyyu ọmọ Haatim, lati ọdọ Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o sọ pe: "Awọn Juu ni awọn ti a binu si, ti awọn Nasara jẹ awọn ẹni anu".
Tirmiziy ni o gba a waAnabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pe dajudaju awọn Juu ni ìjọ kan ti Ọlọhun binu si wọn, nitori pe wọn mọ ododo wọn ko si ṣiṣẹ pẹlu rẹ. Ati pe awọn Nasara ni ìjọ ẹni anu; nitori pe wọn ṣe iṣẹ laini imọ.
Láti ọ̀dọ̀ Abu Huraira- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Awọn Juu ati Kristẹni maa n ka Taoreeta pẹ̀lú èdè Hébérù, wọn si maa n túmọ̀ rẹ pẹlu èdè Lárúbáwá fun awọn Mùsùlùmí, ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa sọ pé: “Ẹ má gba ọ̀rọ̀ àwọn Júù àti Kristẹni ni ododo, ẹ si ma pe e ni irọ, ki ẹ sọ pé: {A gbàgbọ́ nínú Allāhu àti ohun tí Wọ́n sọ̀kalẹ̀ fún wa} [Al-Baqarah: 136] Aayah”.
Bukhaariy gba a waAnọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- kilọ fun awọn ìjọ rẹ láti ṣọ́ra fun gbigba ẹtan pẹ̀lú nǹkan ti àwọn Júù àti Kristẹni n gbà wá nínú àwọn ìwé wọn, Níbi tí àwọn Júù ìgbà ayé Ànábì máa ń ka Taoreeta ní èdè Hébérù. Ó jẹ́ èdè àwọn Júù, wọ́n sì túmọ̀ rẹ̀ ní èdè Lárúbáwá, Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa sọ pé: Ẹ ma gba ọrọ àwọn Júù àti Kristẹni ni ododo, ẹ si ma pe e ni irọ, èyí níbi ohun ti a ko mọ ododo rẹ yatọ si irọ rẹ; Torí pé Ọlọhun ti ọla Rẹ ga pa wa láṣẹ ki a ni igbagbọ ninu Kuraani ati Ìwé ti wọn sọ̀kalẹ̀ fun wọn, ṣùgbọ́n ko si bi a ṣe fẹ mọ èyí tí ó ni àlàáfíà ninu ohun ti wọn n sọ nipa awọn Ìwé sánmọ̀ yẹn yatọ si èyí tí kò ni àlàáfíà; tori ko wa ninu ṣẹria wa ohun ti o maa ṣàlàyé ododo rẹ yatọ si irọ rẹ, Nítorí náà a maa kóra ro, a ko nii gba ọrọ wọn ni ododo; ki a ma baa kópa pẹ̀lú wọn nibi ohun ti wọn yi padà ninu ẹ, a ko si nii pe ọrọ wọn ni irọ; bóyá o le jẹ òdodo, ki a ma baa lọ tako ohun ti wọn pa wa láṣẹ ki a gbagbọ, Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa pa wa láṣẹ ki a sọ pé: “A gbàgbọ́ nínú Allāhu àti ohun tí Wọ́n sọ̀kalẹ̀ fún wa àti ohun tí Wọ́n sọ̀kalẹ̀ fún (àwọn Ànábì) ’Ibrọ̄hīm, ’Ismọ̄‘īl, ’Ishāƙ, Ya‘ƙūb àti àwọn àrọ́mọdọ́mọ Ya‘ƙūb. (A gbàgbọ́ nínú) ohun tí Wọ́n fún (àwọn Ànábì) Mūsā àti ‘Īsā, àti ohun tí Wọ́n fún àwọn Ànábì (yòókù) láti ọ̀dọ̀ Olúwa wọn. A kò ya ẹnì kan sọ́tọ̀ nínú wọn. Àwa sì ni mùsùlùmí (olùjuwọ́-jusẹ̀ sílẹ̀) fún Un.” [Al-Baqarah: 136].
Láti ọ̀dọ̀ Aishah- ki Ọlọhun yọnu si i- pé: Arákùnrin kan jókòó níwájú Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- o wa sọ pé: Irẹ ojiṣẹ Ọlọhun, mo ni àwọn ẹrú kan ti wọn maa n pa irọ́ fun mi, wọn tun maa n janba mi, wọn si tun maa n yapa àṣẹ mi, mo maa n bú wọn, mo si maa n lù wọ́n, báwo ni ọ̀rọ̀ mi ati wọn ṣe maa jẹ ni ọdọ Ọlọhun? O sọ pe: “Wọ́n maa ṣírò ijanba ti wọn ṣe fun ẹ, ati bi wọn ṣe yapa àṣẹ rẹ, ati irọ́ ti wọn pa fun ẹ, ati ìyà ti o fi jẹ wọn, tí ìyà ti o fi jẹ wọn ba jẹ odiwọn ẹṣẹ wọn, a jẹ pe o ti ṣe déédéé ara wọn, o o nii ni ẹsan, o o si nii jẹ ìyà, ṣùgbọ́n ti iya ti o fi jẹ wọn ba kere si ẹṣẹ wọn, ìyẹn maa jẹ alekun fun ẹ, ṣùgbọ́n ti iya ti o fi jẹ wọn ba ju ẹṣẹ wọn lọ, wọn maa gba ẹ̀san alekun naa lara rẹ fun wọn”, o sọ pe: Ni arákùnrin naa wa rìn jìnnà, ni o ba bẹ̀rẹ̀ si nii sunkún ti o si n pariwo, ni ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa sọ pé: “Ṣe o o ka tira Ọlọhun ti o sọ pe: {A máa gbé àwọn òṣùwọ̀n déédé kalẹ̀ ní Ọjọ́ Àjíǹde. Nítorí náà, wọn kò níí ṣe àbòsí kiní kan fún ẹ̀mí kan}, aaya”, ni arákùnrin naa wa sọ pé: Mo fi Ọlọhun bura irẹ ojiṣẹ Ọlọhun, mi o ri ohun ti o loore fun emi ati awọn ju ki a pínyà lọ, mo n fi ọ jẹ́rìí pe gbogbo wọn ti di olómìnira.
Tirmiziy ni o gba a waArákùnrin kan wa ba Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- lati wa fi ẹjọ́ bi àwọn ẹrú rẹ ṣe n hùwà sùn, pe wọn maa n pa irọ́ fun un, wọn si maa n janba rẹ nibi agbafipamọ, wọn si maa n rẹ́ ẹ jẹ nibi ibalopọ, wọn si maa n yapa àṣẹ rẹ, oun naa si maa n bu wọn, o si maa n na wọn lati kọ́ wọn ni ẹ̀kọ́, o wa bi i leere nipa bi ọrọ oun ṣe maa jẹ pẹlu wọn ni Ọjọ́ Àjíǹde? Ni Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa sọ pé: Wọ́n maa ṣírò ijanba ti wọn ṣe fun ẹ, ati bi wọn ṣe yapa àṣẹ rẹ, ati irọ́ ti wọn pa fun ẹ, ati ìyà ti o fi jẹ wọn, tí ìyà ti o fi jẹ wọn ba jẹ odiwọn ẹṣẹ wọn, o o nii ni ẹsan, o o si nii jẹ ìyà, tí iya ti o fi jẹ wọn ba kere si ẹṣẹ wọn, o maa jẹ alekun ẹsan fun ẹ, ṣùgbọ́n ti iya ti o fi jẹ wọn ba ju ẹṣẹ wọn lọ, wọn maa fi iya jẹ ìwọ naa, wọn si maa gba odiwọn ti o ba le lọ́wọ́ rẹ, wọn si maa fun wọn, ni arákùnrin naa wa rìn jìnnà, o wa bẹ̀rẹ̀ si nii n sunkún ti o si n pariwo, ni ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa sọ fún un pé: Ṣé o o ka tira Ọlọhun ti o sọ pe: {A máa gbé àwọn òṣùwọ̀n déédé kalẹ̀ ní Ọjọ́ Àjíǹde. Nítorí náà, wọn kò níí ṣe àbòsí kiní kan fún ẹ̀mí kan. Kí (iṣẹ́) jẹ́ ìwọ̀n èso kardal (bín-íntín), A máa mú un wá. A sì tó ní Olùṣírò} [Al-Anbiyaa: 47], wọn kò níí ṣe àbòsí kiní kan fún ẹni kankan ni Ọjọ́ Àjíǹde, àwọn òṣùwọ̀n si maa wa laarin awọn èèyàn pẹ̀lú déédéé, ni arákùnrin naa wa sọ pé: Mo fi Ọlọhun bura irẹ ojiṣẹ Ọlọhun, mi o ri nǹkan kan ti o ni ọla fun èmi ati awọn ju ki a pínyà lọ, mo n fi ọ jẹ́rìí pe gbogbo wọn ti di ọmọlúwàbí nítorí tí Ọlọhun; ni ti ipaya ìṣirò ati ìyà.
Lati ọdọ Ubay ọmọ Kahb- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Òjíṣẹ́ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: “Irẹ Abu Al-Munzir, ǹjẹ́ o mọ aaya wo ninu tira Ọlọhun ti o wa pẹlu rẹ ni o tobi julọ?”, o sọ pe: Mo sọ pé: Ọlọhun ati ojiṣẹ Rẹ ni wọn ni imọ julọ. O sọ pe: “Irẹ Abu Al-Munzir, ǹjẹ́ o mọ aaya wo ninu tira Ọlọhun ti o wa pẹlu rẹ ni o tobi julọ?”, o sọ pe: Mo sọ pé: {Allāhu, kò sí ọlọ́hun kan tí ìjọ́sìn tọ́ sí àfi Òun, Alààyè, Alámòjúútó-ẹ̀dá} [Al-Baqarah: 255]. O sọ pe: O wa fi ọwọ́ lu mi láyà, o wa sọ pé: “Mo fi Ọlọhun búra, o kú oriire imọ naa, ki Ọlọhun ṣe e ni irọrun fun ẹ, irẹ Abu Al-Mundhir”.
Muslim gba a waAnọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- bi Ubay ọmọ Kahb léèrè nipa aaya ti o tobi ju ninu tira Ọlọhun, o wa ṣe iyèméjì nibi dáhùn, lẹ́yìn náà ni o wa sọ pé: Oun ni aayatul Kursiyy: {Allāhu, kò sí ọlọ́hun kan tí ìjọ́sìn tọ́ sí àfi Òun, Alààyè, Alámòjúútó-ẹ̀dá}, Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa ṣe atilẹyin fun un, Anọbi wa lu u ni àyà lati tọka si pe o kún fun imọ ati ọgbọ́n, o wa ṣe adua fun un pe ki o maa dunnu pẹ̀lú imọ yii ki o si rọrùn fún un.
Lati ọdọ Az-Zubair ọmọ Al-Awwaam, o sọ pe: Nigba ti (Thumma latus alunna yauma-izin ‘anin na’eem) sọkalẹ (At-Takathur: 8), Az-Zubair sọ pe: Irẹ Ojiṣẹ Ọlọhun, idẹra wo ni wọn maa bi wa leere nipa rẹ, dajudaju mejeeji ni dudu meji, eso dabinu ati omi? O sọ pe: “Oun naa ni o maa jẹ”.
Tirmiziy ni o gba a waNigba ti ayah sọkalẹ: (Thumma latus alunna yauma-izin ‘anin na’eem) o n túmọ̀ si pe: Wọn maa pada beere lọwọ wọn nipa idupẹ lori nnkan ti Ọlọhun ṣe ni idẹra le wọn lori ninu awọn idẹra, Az-Zubair ọmọ Al-‘Awwam- ki Ọlọhun yọnu si i- sọ pe: Irẹ Ojiṣẹ Ọlọhun, idẹra wo ni wọn maa bi wa leere nipa rẹ? Dajudaju idẹra mejeeji ko kii ṣe nnkan ti wọn le bukaata si ibeere ati pe mejeeji ni eso dabinu ati omi! Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pe: Dajudaju wọn maa bi yin leere nipa idẹra pẹlu isẹsi yii ti ẹ wa nibẹ yìí, nitori pe mejeeji jẹ idẹra nla meji ninu awọn idẹra Ọlọhun- ti ọla Rẹ ga-.
Lati ọdọ Aishah- ki Ọlọhun yọnu si i- o sọ pe: Ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ka aaya yii: {Òun ni Ẹni tí Ó sọ Tírà kalẹ̀ fún ọ; àwọn āyah aláìnípọ́n-na wà nínú rẹ̀ - àwọn sì ni ìpìlẹ̀ Tírà -, onípọ́n-na sì ni ìyókù. Ní ti àwọn tí ìgbúnrí kúrò níbi òdodo wà nínú ọkàn wọn, wọn yóò máa tẹ̀lé èyí t’ó ní pọ́n-na nínú rẹ̀ láti fi wá wàhálà àti láti fí wá ìtúmọ̀ (òdì) fún un. Kò sì sí ẹni t’ó nímọ̀ ìtúmọ̀ rẹ̀ àfi Allāhu. Àwọn àgbà nínú ìmọ̀ ẹ̀sìn, wọ́n ń sọ pé: “A gbà á gbọ́. Láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa ni gbogbo rẹ̀ (ti sọ̀kalẹ̀).” Kò sí ẹni t’ó ń lo ìrántí àyàfi àwọn onílàákàyè} [Aal Imraan: 7]. O sọ pe: Òjíṣẹ́ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: “Ti o ba ti ri awọn ti n tẹle ohun ti o ruju ninu ẹ, àwọn ti Ọlọhun sọ nìyẹn, ki ẹ ṣọ́ra fun wọn”.
Ohun ti wọ́n fi ẹnu kò lé lórí niOjiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ka aaya yii: {Òun ni Ẹni tí Ó sọ Tírà kalẹ̀ fún ọ; àwọn āyah aláìnípọ́n-na wà nínú rẹ̀ – àwọn sì ni ìpìlẹ̀ Tírà -, onípọ́n-na sì ni ìyókù. Ní ti àwọn tí ìgbúnrí kúrò níbi òdodo wà nínú ọkàn wọn, wọn yóò máa tẹ̀lé èyí t’ó ní pọ́n-na nínú rẹ̀ láti fi wá wàhálà àti láti fí wá ìtúmọ̀ (òdì) fún un. Kò sì sí ẹni t’ó nímọ̀ ìtúmọ̀ rẹ̀ àfi Allāhu. Àwọn àgbà nínú ìmọ̀ ẹ̀sìn, wọ́n ń sọ pé: “A gbà á gbọ́. Láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa ni gbogbo rẹ̀ (ti sọ̀kalẹ̀).” Kò sí ẹni t’ó ń lo ìrántí àyàfi àwọn onílàákàyè}. Inú rẹ ni Ọlọhun ti sọ pé Oun ni O sọ Kuraani kalẹ fun Anọbi Rẹ, eyi ti o ni àwọn aaya ti itumọ wọn ko ruju, ti a si mọ idajọ wọn, àwọn ni ipilẹ tira naa ati ibuṣẹrisi rẹ, àwọn naa ni ibuṣẹrisi nígbà tí a ba yapa, o tun n bẹ ninu rẹ àwọn aaya miiran ti a le fun ni itumọ oríṣiríṣi, ti itumọ wọn maa n daru lójú àwọn èèyàn kan, tàbí ki o maa lero pe atako n bẹ láàrin rẹ ati aaya mìíràn, lẹyin naa ni Ọlọhun wa ṣàlàyé bi àwọn èèyàn ṣe n lo pẹ̀lú àwọn aaya yii, àwọn ti igbunri kuro nibi òdodo n bẹ ninu ọkan wọn maa fi eyi ti ko ruju silẹ, wọn maa wa gba eyi ti o ruju mu, lati fi le da iruju silẹ ati lati le ṣi àwọn èèyàn lọ́nà, wọn a si maa yi itumọ rẹ pada si ohun ti o maa ba ifẹ-inu wọn mu, ṣùgbọ́n àwọn ti ẹsẹ wọn rinlẹ ninu imọ maa mọ eyi ti o ruju yii, wọn maa wa da a pada sibi eyi ti ko ruju, wọn si maa gba a gbọ pe ọdọ Ọlọhun ti ọla Rẹ ga ni o ti wa, kò si rọrùn ki o daru tabi tako ara wọn, ṣùgbọ́n Kò sí ẹni t’ó ń lo ìrántí àyàfi àwọn onílàákàyè ti o ni alaafia. Lẹ́yìn naa ni Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa sọ fun iya àwọn mumini, Aishah- ki Ọlọhun yọnu si i- pe ti o ba ti ri awọn ti n tẹle eyi ti o ruju, àwọn yẹn ni Ọlọhun sọ ninu ọ̀rọ̀ Rẹ pe: {Ní ti àwọn tí ìgbúnrí kúrò níbi òdodo wà nínú ọkàn wọn}, ki ẹ ṣọ́ra fun wọn, ki ẹ si ma tẹti si wọn.
Lati ọdọ ọmọ ‘Umar – ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji: Dajudaju Ojiṣẹ Ọlọhun – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – ba awọn eeyan sọrọ ni ọjọ ti wọn ṣi Makkah, ni o wa sọ pe: «Mo pe ẹyin eeyan, dajudaju Ọlọhun ti gbe kuro fun yin igberaga igba aimọkan ati ṣiṣe iyanran wọn pẹlu awọn baba wọn, nitori naa meji ni awọn eeyan: eniire olupaya alapọn-ọnle lọdọ Ọlọhun, ati onibajẹ oloriibu ẹni yẹpẹrẹ lọdọ Ọlọhun, awọn eeyan, ọmọ Anabi Aadam ni wọn, ti Ọlọhun si da Aadam lati ibi erupẹ, Ọlọhun sọ pe: {Ẹ̀yin ènìyàn, dájúdájú Àwa ṣẹ̀dá yín láti ara ọkùnrin àti obìnrin. A sì ṣe yín ní orílẹ̀-èdè orílẹ̀-èdè àti ìran-ìran nítorí kí ẹ lè dára yín mọ̀. Dájúdájú alápọ̀n-ọ́nlé jùlọ nínú yín lọ́dọ̀ Allāhu ni ẹni t’ó bẹ̀rù (Rẹ̀) jùlọ. Dájúdájú Allāhu ni Onímọ̀, Alámọ̀tán} [Al-Hujrāt: 13]».
Tirmiziy ni o gba a waAnabi – ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a – ba awọn eeyan sọrọ ni ọjọ ti wọn ṣi Makkah, o wa sọ pe: Mo pe ẹyin eeyan dajudaju Ọlọhun ti gbe kuro fun yin igberaga igba aimọkan ati ijọra-ẹni-loju rẹ, ati fifi awọn baba ẹni ṣe iyanran, ati pe awọn eeyan iran meji ni wọn: Ninu ki o jẹ Mumini eniire olupaya Ọlọhun olutẹle aṣẹ ti n jọ́sìn fun Ọlọhun, eleyii alapọn-ọnle ni lọdọ Ọlọhun, koda ki o ma jẹ ẹni ti o ni ipo ati iran lọdọ awọn eeyan. Tabi ki o jẹ keferi onibajẹ oloriibu, eleyii ẹni yẹpẹrẹ ti ko ni asunsi ni lọdọ Ọlọhun, ti ko si ja mọ nkankan, koda ko jẹ abiyi ti o ni ipo ati ọla. Ati pe gbogbo eeyan pata ọmọ Anabi Aadam ni wọn, ti Ọlọhun si da Aadam lati ibi erupẹ, nitori naa ko lẹtọọ fun ẹni ti ipilẹ rẹ jẹ erupẹ ki o ṣe igberaga ati ijọra-ẹni-loju, ati pe nkan ti o fi idi iyẹn mulẹ ni gbolohun Ọlọhun ti O tobi ti O gbọnngbọn to sọ pe: {Ẹ̀yin ènìyàn, dájúdájú Àwa ṣẹ̀dá yín láti ara ọkùnrin àti obìnrin. A sì ṣe yín ní orílẹ̀-èdè orílẹ̀-èdè àti ìran-ìran nítorí kí ẹ lè dára yín mọ̀. Dájúdájú alápọ̀n-ọ́nlé jùlọ nínú yín lọ́dọ̀ Allāhu ni ẹni t’ó bẹ̀rù (Rẹ̀) jùlọ. Dájúdájú Allāhu ni Onímọ̀, Alámọ̀tán} [Al-Hujrāt: 13].